Orin Dafidi 50:1-23

Lesson 204 - Senior

Memory Verse
AKỌSORI: “Ẹnikẹni ti o ba ru ẹbọ iyìn, o yìn mi logo: ati ẹniti o ba mu ọna ọrọ rè̩ tọ li emi o fi igbala Ọlọrun hàn fun” (Orin Dafidi 50:23).
Cross References

I Ọlá Nlá Ọlọrun

1. Ọlọrun kari gbogbo ayé, Orin Dafidi 50:1

2. Ofin Rè̩ n jade lọ lati Sioni, Orin Dafidi 50:2

3. Ajonirun iná ni Ọlọrun, Orin Dafidi 50:3

4. A pe awọn eniyan mimọ ni Ọrun ati ni ayé lati jẹri si Israẹli, Orin Dafidi 50:4-7

II Ọlọrun Bá Israẹli Wíjọ

1. Ẹbọ òde ara nikan kò tó, Orin Dafidi 50:8-13

2. Ọpé̩, è̩jé̩ ati adura atinuwa jé̩ dídùn inú Ọlọrun, Orin Dafidi 50:14, 15

III Ìdájọ lori Ìwà Buburu

1. Ọlọrun kọ ìwà agabagebe, Orin Dafidi 50:16, 17

2. Awọn agabagebe jẹbi olè jíjà, panṣaga ati ọrọ ibanijẹ, Orin Dafidi 50:18-20

3. Aimu idájọ ṣẹ kankan kò fi hàn pé Ọlọrun fé̩ ìwà buburu, Orin Dafidi 50:21, 22

IV Ìfé̩ Ọlọrun

1. Ìyìn gbé ogo Ọlọrun ga, Orin Dafidi 50:23

2. Ọrọ tabi ìrìn wa ni lati jé̩ pípé, Orin Dafidi 50:23.

Notes
ALAYÉ

Ọlá Nlá Ọlọrun

“Ọlọrun Olodumare, ani OLUWA, li o ti sọrọ.” Ọlọrun Israẹli kò dabi awọn oriṣa orilẹ-ède ti o yí wọn ká. Oun ni Ọlọrun agbayé, Ẹlẹda ohun gbogbo. “Tali o ti wọn omi ni kòto-ọwọ rè̩, ti o si ti fi ika wọn ọrun, ti o si ti kó erùpẹ aiye jọ sinu òṣuwọn, ti o si fi ìwọn wọn awọn oke-nla, ati awọn oke kékèké ninu òṣuwọn?” “Gbe oju nyin soke sibi giga, ki ẹ si wò, tali o dá nkan wọnyi, ti nmu ogun wọn jade wá ni iye: o npè gbogbo wọn li orukọ nipa titobi ipá rè̩, nitoripe on le ni ipá; kò si ọkan ti o kù … Iwọ kò ti imọ? iwọ kò ti igbọ, pe, Ọlọrun aiyeraiye, OLUWA, Ẹlẹda gbogbo ipẹkun aiye, kì iṣārè̩, bḝni ārè̩ ki imu u? kò si awari oye rè̩” (Isaiah 40:12, 26, 28).

Ọlọrun gbogbo ayé, Oun naa ni Ọlọrun kan naa ti O ti yan Israẹli ti O si fi Sioni ṣe olori ibùgbé Rè̩. “Lati Sioni wá, pipé ẹwà, Ọlọrun ti tan imọlẹ.” Awọn Ọmọ Israẹli ni a fi oju rere hàn fun ju gbogbo eniyan agbayé lọ, lati ni Ọlọrun alagbara gẹgẹ bi Ọlọrun wọn. A fi titobi Rè̩ hàn laaarin wọn nigbà ti O fun wọn ni ofin lori oke Sinai. “Iwò ogo OLUWA dabi iná ajonirun li ori òke na li oju awọn ọmọ Israẹli” (Ẹksodu 24:17). “Oke Sinai si jé̩ kiki ẽfi, nitoriti OLUWA sọkalẹ sori rè̩ ninu iná: ẽfi na si goke bi ẽfi ileru, gbogbo oke na si mìtiti” (Ẹksodu 19:18).

O dara fun wa lati mọ pé a n sin Ọlọrun kan naa lonii. Ẹ jé̩ ki a ṣe àṣàrò nipa Rè̩ ki a si gbiyanju lati ri fìrí titobi Rè̩ ati agbara Rè̩. Èrò yii pé, Ẹni ti o fi ọrọ ẹnu Rè̩ dá ayé yoo feti si igbe wa yoo si dahùn è̩bè̩ wa, bi o ti wu ki o kéré tó, yẹ ki o mú wa kún fun ìrè̩lè̩ ati ifé̩ si I. O fi ìfé̩ nlá Rè̩ hàn ni ti pe O rán Ọmọ Rè̩ lati kú ki a le yọ wa kuro ninu ọnà è̩ṣè̩ wa. Njẹ a kò jẹ Ẹ ni igbese iyin ati idupẹ titi ayeraye?

Fífi Ẹbọ Dá Majẹmu

Onisaamu ṣe apejuwe bi Ọlọrun alagbara ti n pe awọn eniyan mimọ ni Ọrun ati ni ayé lati jẹri si idajọ òdodo Rè̩ lori Israẹli. “Kó awọn enia mimọ mi jọ pọ si ọdọ mi: awọn ti o fi ẹbọ ba mi da majẹmu.” Awọn eniyan mimọ Ọlọrun tootọ ni awọn ti o ti fi ẹbọ bá Ọlọrun dá majẹmu. Nigbà ti eniyan bá mọ riri iyè ainipẹkun, kò si iye ti o ga ju lati fi ra a. Ki ni ohun ti o ṣọwọn tó bẹẹ ti o le maa mú eniyan lọra, bi o bá jé̩ pé Ọlọrun n beere rè̩? Ọkẹ aimoye awọn ajẹriku ni kò ka ẹmí wọn si, ki wọn ba le jé̩ oloootọ si Kristi. È̩jè̩ wọn yoo ha jẹri gbe awọn ti o n kọ lati fi ara wọn fun Ọlorun ni ẹbọ aayè, mimọ, fun ìsìn Rè̩? Ọlọrun n fé̩ ki a le fi tifẹtifẹ kọ iya, baba, arabinrin tabi arakunrin, ki a sọ ẹmí wa paapaa nù, bi o bá gbà bẹẹ, ki awa ki o le jé̩ oloootọ ati olododo si Ẹni ti o pè wa. Jesu wi pé, “Bi ẹnikan ba nfẹ lati tọ mi lẹhin, ki o sẹ ara rè̩, ki o si gbé agbelebu rè̩, ki o si mā tọ mi lẹhin” (Matteu 16:24).

Ọkunrin kan tọ Jesu wá nigbà kan pẹlu awọn ọrọ wọnyii, “Oluwa, emi nfẹ lati mā tọ ọ lẹhin; ṣugbọn jẹki nkọ …” Jesu si dahùn pe, “Kò si ẹni, ti o fi ọwọ rè̩ le ohunelo itulẹ, ti o si wò ẹhin, ti o yẹ fun ijọba Ọlọrun” (Luku 9:62). Awọn miiran n fẹ sin Ọlọrun ti wọn bá lè kọ lọ ṣe awọn ohun wọnni ti ọkàn wọn n fé̩. Ọlọrun n pe gbogbo awọn ti o bá fé̩ sin In lati ba A fi ẹbọ dá majẹmu. Wọn ni lati pinnu lati fi awọn nnkan wọnni silẹ ti o ná wọn ni owó gẹgẹ bi Dafidi ìgbà nì ti ki yoo rú ẹbọ ti kò ni ná an ni owó si Oluwa.

È̩sùn tí A fi Kan Israẹli

Ọlọrun fi hàn gbangba fun Israẹli pe ki i ṣe pe Oun fé̩ ẹbọ wọn ni Oun ṣe n mú wọn wá si idajọ. “Bi ebi npa mi, Emi ki yio sọ fun ọ: nitori pe aiye ni ti emi, ati ẹkún inu rè̩.” Ọlọrun kò bá Israẹli wí nitori wọn kò sun ọrẹ ẹbọ sisun – eyi nì paapaa tó ohun tí ó lè mú ijiya wá. È̩sùn ti a fi wọn sùn ni pe wọn kò san è̩jé̩ wọn, wọn kò si ni ọkàn idupẹ si Ọlọrun.

Ẹbọ Wa si Ọlọrun

Lonii, Ọlọrun kò fé̩ awọn ohun ìní wa; Oun kò si fé̩ ọrọ wa; Oun kò fé̩ maluu wa tabi ohunkohun ti o jé̩ ohun ìní wa ti o n ṣegbe. S̩ugbọn awa ni a kò lè wà lai si Ọlọrun! Ọlọrun fun wa ni agbara lati kó awọn ohun alumọni ayé yii jọ; nitori naa lọdọ Rè̩ ni a ti ri gbogbo ohun ti a ni gbà, i baa ṣe ibukun ti Ẹmi tabi ti ara. Bí Oun bá n fẹ maluu, O le sọkalẹ ki O si mú wọn lati ẹgbẹrun òkè.

Iwọ ha wi pé, “Njẹ bi Ọlọrun kò ba fẹ ohun ìní mi, akoko mi, talẹnti mi, ki ni mo ha n fi fun Un si? Ki ni ṣe ti mo ni lati fi ara mi rubọ fun Un?” Ti Rè̩ ni ohun gbogbo i ṣe. Bi a bá ni talẹnti, agbara tabi ipá, lati ọdọ Ọlọrun ni gbogbo wọn ti wá. “Gbogbo è̩bun rere ati gbogbo è̩bun pipé lati oke li o ti wá, o si nsọkalẹ lati ọdọ Baba imọlẹ wá” (Jakọbu 1:17). Iriju lasan ni a jé̩ lori gbogbo ìní ati è̩bùn ti Ọlọrun fi fun wa; kò ha yẹ ki a ni ọkàn imoore to bẹẹ ti a o fi dá awọn è̩bùn wọnni pada fun Un nipa lilo wọn fun iṣé̩ Rè̩? Dajudaju a kò fé̩ gbọ ibawi nì pe, “Ẹ gbé alailere ọmọ-ọdọ na sọ sinu òkunkun lode.”

Olukuluku wa ni yoo jihin fun Ọlọrun ni ọjọ kan nipa bi a ti lo awọn ohun wọnni ti Ọlọrun fi si itọju wa. Ihinrere n tè̩ siwaju lonii. Njé̩ iwọ jé̩ alabapin ninu iṣẹ naa? Njé̩ iwọ n ṣe iranlọwọ lati mú ẹrù naa fúyé̩ fun awọn ti o wà loju ogun? Njé̩ iwọ n fi awọn è̩bùn, talẹnti ati awọn ohun wọnni ti Ọlọrun fi fun ọ si arọwọto fun Ọlọrun lati lò? Bi o kò tilẹ ṣe bẹẹ, Ihinrere yoo maa tẹ siwaju; ṣugbọn boya ọkàn kan ti o wà lọwọ ọtún rẹ ati ekeji lọwọ òsì rẹ, ki yoo gbọ ihin igbala nitori iwọ kùnà lati sa ipá ti rẹ. Oṣiṣẹ ṣọwọn lonii ju ti atẹyinwa lọ; ikore oko pọn, Oluwa si n beere pe, “Tali emi o rán?” Njé̩ iwọ wà lara awọn ti o n wi pé, “Jẹ ki nkọ …?” (ṣe eyi tabi eyi nì). Iṣẹ Oluwa kò gbọdọ duro! O ni lati jé̩ ohun ekinni ninu igbesi-ayé rẹ. Ipè ikẹyin fun awọn alagbaṣe n kọja lọ. Jé̩ ipè naa lonii.

Olugbala

“Ki o si kepè mi li ọjọ ipọnju: emi o gbà ọ, iwọ o si ma yìn mi logo.” Nigbà pupọ ni o ṣe pe aiṣedeedee eniyan ni o n fà á sinu iyọnu. Bi eyi ba ri bẹẹ, Ọlọrun ti ṣeleri pe bi a bá lè ké pe Oun ni ọjọ ìpọnjú, Oun yoo gbà wa. Ọkàn wa ni lati kún fun ọpé̩ si irú Ọlọrun bayii.

Afarawe Iwa-Bi-Ọlọrun

Fun awọn ti o ṣe pe ètò ìsìn lasan ni wọn kan n tẹle – ti wọn kan n fi ẹnu lasan sọ nipa majẹmu Ọlọrun ti wọn si n waasu ofin Rè̩ - Ọlọrun fi è̩ṣẹ ti wọn n dá hàn gedegbe. Wọn n bá olè dimọ pọ, boya wọn tilẹ n ra ọjà ti ó jí. Wọn jẹbi panṣaga, è̩ṣẹ ti awọn ẹlẹsin miiran tilẹ fara mọ lode oni. Nitori eyi ni wọn ṣe bé̩ Johannu Baptisti lori nitori o sọ gbangba fun Hẹrodu pe kò tọ fun un lati fé̩ iyawo arakunrin rè̩. Wọn si tún jẹbi sisọ ọrọ buburu ati èkè. Wọn n ṣaata arakunrin wọn. Gbogbo eyi ni wọn n ṣe, wọn lero pe wọn le ri “oju rere” Ọlọrun nipa mímú ẹbọ wá lai si ironupiwada atọkanwa.

Fifa Idajọ Sẹyin

“Nitoriti a kò mu idajọ ṣẹ kánkán si iṣẹ buburu, nitorina aiya awọn ọmọ enia mura pāpa lati huwa ibi” (Oniwasu 8:11). “Nkan wọnyi ni iwọ ṣe, emi si dakẹ” (Orin Dafidi 50:21). Oluwa ninu aanu Rè̩, fun ọmọ eniyan ni anfaani lati wá si ironupiwada; ṣugbọn bi o bá kọ lati ronupiwada, idajọ dájú. Israẹli lero pé Ọlọrun jé̩ alakẹbajé̩ bi ti wọn. Wọn rò pé a kò ri è̩ṣè̩ wọn ati pé Ọlọrun ki yoo jé̩ eniyan buburu niyà. Ọlọrun sọ fun Israẹli pe ìdájọ yoo wá, wọn yoo si ri i. “A kò le gàn Ọlọrun: nitori ohunkohun ti enia ba funrugbin, on ni yio si ká” (Galatia 6:7). Ọlọrun rán ìkìlọ líle si awọn Ọmọ Israẹli nitori ọnà ajambaku ti wọn gbà n sìn, ati igbesi-ayé ibajé̩ ti wọn n gbé. “Njẹ rò eyi, ẹnyin ti o gbagbe Ọlọrun, ki emi ki o má ba fà nyin ya pẹrẹ-pẹrẹ, ti kò si olugbala.” Pẹlu gbogbo ìkìlọ líle yii, ọnà aanu ṣi silẹ: “Ẹnikẹni ti o ba ru ẹbọ iyìn, o yìn mi logo: ati ẹniti o ba mu ọna ọrọ rè̩ tọ li emi o fi igbala Ọlọrun hàn fun.”

Igbesi-Ayé Ailẹṣè̩

Ọlọrun ní inú dídùn si aanu, O sì fé̩ iyìn, ṣugbọn kò si ohun ti o lè dipo rinrin deedee. Kò si ohun ti a lè fi dipo igbesi-ayé ti kò ni è̩ṣè̩. Kò si ẹni ti o lè rú ẹbọ ọpé̩ si Ọlọrun gẹgẹ bi ẹni ti a ti wè̩ ninu È̩jè̩ Ọdọ-Agutan, ti igbesi-ayé rè̩ si jé̩ ailẹgan. Jẹ ki ẹni irapada Oluwa ki o fi iyìn fun Un; ki o si dupé̩ fun igbala nlá Rè̩.

Questions
AWỌN IBEERE
  1. Ki ni itumọ dídá majẹmu pẹlu ẹbọ?
  2. Wá awọn ẹsẹ Iwe Mimọ ti o ṣapejuwe titobi Ọlọrun.
  3. Ki ni pataki è̩sùn ti a fi Israẹli sùn?
  4. Ki ni awọn ileri ti o wà ni orí ìwè yii?
  5. Ki ni awọn ileri wọnyii rọ mọ?
  6. Ki ni itumọ “ọrọ” ni ẹsẹ kẹtalelogun?
  7. Èwo ninu ofin mẹwaa ni Ọlọrun sọ pe eniyan buburu ti rú?
  8. Ki ni Ọlọrun fé̩ ki Israẹli ki o ṣe?